Ìpàdé Àpapọ̀ Gbogbogbò
Jíjẹ́-Ọmọlẹ́hìn Alágbára ní Àwọn Ọjọ́ Ìkẹhìn
Ìpàdé Àpapọ̀ Gbogbogbò Oṣù Kẹ́rin 2022


Jíjẹ́-Ọmọlẹ́hìn Alágbára ní Àwọn Ọjọ́ Ìkẹhìn

Ẹ jẹ́ kí a ní ìgboyà, kí a máa ṣe àforíjì, jẹ́ akíkanjú, má ṣe tijú, olõtọ́, kí a má ṣe bẹ̀rù bí a ṣe ngbé ìmọ́lẹ̀ Olúwa dúró ní àwọn ọjọ́ ìkẹhìn wọ̀nyí.

Ìwà agbára òmìnira jẹ́ ẹ̀bùn iyebíye kan.1 A wà ní òmìnira láti yan ìdásílẹ̀ àti ìyè àìnípẹ̀kun, nípa Onílàjà nlá ti gbogbo ènìyàn, tàbí láti yan ìgbèkùn àti ikú, gẹ́gẹ́bí ìgbèkùn àti agbára ti èṣù.”2 Ọlọ́run kò lè fi ipá mú wa láti ṣe rere, àti pé èṣù náà kò lè fi ipá mú wa láti ṣe ibi.3 Bíótilẹ̀jẹ́pé àwọn kan lè rò pé ikú jẹ́ ìjà láàárín Ọlọ́run àti ọ̀tá, ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ Rẹ̀ “a sì pa Sátánì lẹ́nu mọ́ a sì lé e kúrò. … Agbára [wa] ni a ndánwò—kì í ṣe ti Ọlọ́run.”4

Ní ìparí àwa yìó gba èrè àwọn ohun àṣàyàn tí ìgbésí ayé wa ti a gbìn.5 Nítorínáà kí ni àpapọ̀ àwọn èrò, àwọn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, àwọn ọ̀rọ̀, àti àwọn iṣẹ́ wa sọ nípa ìfẹ́ wa fún Olùgbàlà, àyànfẹ́ ìránṣẹ́ Rẹ̀, àti Ìjọ Rẹ̀ tí a mú padàbọ̀sípò? Njẹ ìrìbọmi wa, oyèàálùfà, àti àwọn májẹ̀mú tẹ́mpìlì túmọ̀ sí díẹ̀ síi fún wa ju ìyìn àgbáyé lọ tàbi iye àwọn “ìfẹ́” lórí àwùjọ ìròhìn bi? Njẹ́ ìfẹ́ wa fún Olúwa àti àwọn òfin Rẹ̀ lágbára ju ìfẹ́ wa fún ohunkóhun tàbí ẹlòmíràn ní ayé yí bí?

Ọ̀tá àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ ti nwá nígbàgbogbo láti pa àwọn iṣẹ́ Krístì àti àwọn wòlíì Rẹ̀ run. Àwọn òfin Olùgbàlà, tí a kò bá paátì pátápátá, ni a ti sọ di asán sí àìnítumọ̀ nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú ayé òde òní. Àwọn òjíṣẹ́ Ọlọ́run tí wọ́n nkọ́ àwọn òtítọ́ “àìrọnilọ̀rùn” nígbàgbogbo ni a dàsílẹ̀. Àní Olùgbàlà fúnraarẹ̀ ni a pè ní “ọkùnrin ọ̀jẹun, àti ọ̀mùtí,”6 wọ́n fi ẹ̀sùn kàn án pé o nda èrò ará-ìlú láàmú àti pé o nfa ìpinyà. Àwọn ọkàn aláìlera tí wọ́n sì jẹ́ ọ̀wọ́n “gbìmọ̀ pọ̀ bí wọ́n ṣe lè dì í mú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀,”7 àti pé “ẹ̀ya ẹ̀sìn” Rẹ̀ ti àwọn Kristẹni ìbẹ̀rẹ̀ wà “níbi gbogbo … tí a sọ̀rọ̀ ní ìlòdì sí.”8

Olùgbàlà àti àwọn àtẹ̀lé Rẹ̀ àkọ́kọ́ kojú àtakò líle nínú àti nìta, a sì nní ìrírí kannáà. Loni kò fẹ́rẹ̀ ṣeéṣe láti fi ìgboyà gbé ìgbésí ayé ìgbàgbọ́ wa láìsí fífàmọ́ra díẹ̀ nínú àwọn ìka ẹ̀gàn àti ìfojúhàn lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan láti ayé. Fífi ìgboyà tẹ̀lé Olùgbàlà ní èrè, ṣùgbọ́n àwọn ìgbà míràn a lè mú nínú àwọn irun orí tí àwọn wọnni tó nṣàgbàwí “jẹ, mu, àti láti ṣe àríyá”9 ìmòye, níbití ìgbàgbọ́ nínú Krístì, ìgbọràn, àti ìrònúpìwàdà tí a rọ́pò pẹ̀lú ìròbìnújẹ́ pé Ọlọ́run yíò dá ẹ̀ṣẹ̀ díẹ̀ láre nítorí pé ó nífẹ wa púpọ̀.

Sísọ̀rọ̀ “nípa ohùn [Rẹ] tàbí nípa ohùn àwọn ìránṣẹ́ [Rẹ],”10 ṣé Olùgbàlà kò sọ nípa ọjọ́ wa pé “àkokò yíò dé nígbàtí wọ́n kì yíò faradà ẹ̀kọ́ tí ó jinlẹ̀; ṣùgbọ́n ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara wọn, wọn yíò kó àwọn olùkọ́ jọ fún ara wọn” àti pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ “yíò yí etí wọn padà kúrò nínú òtítọ́, wọn yíò sì yí padà sí ìtan-ẹ̀tàn”?11 Kò ha ṣọ̀fọ̀ pé lásán ni wọ́n njọ́sìn sími, tí wọ́n nkọ́ni fún ẹ̀kọ́ àwọn òfin ènìyàn”?12 Kò ha kìlọ̀ pé “láti ara yín fúnra yín ni àwọn ènìyàn yíò dìde, wọn yíò sì máa sọ àwọn ohun àyídáyidà, láti fa àwọn ọmọẹ̀hìn lọ sẹ́hìn wọn”?13 Kò ha ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ibi [ni a o pè ní] rere àti rere ni ibi,”14 àti pé “àwọn ọ̀tá ènìyàn ni yíò jẹ́ àwọn ará ilé ti ararẹ̀”?15

Nítorínáà kílówá nípa wa? Ṣé ó yẹ ká máa fòyà tàbí kí ẹ̀rù máa bà wá? Ṣé ó yẹ kí á gbé ẹ̀sìn wa ní ìjìnlẹ̀ periscope bí? Dájúdájú bẹ́ẹ̀kọ́! Pẹ̀lú ìgbàgbọ́ nínú Krístì, a kò ní láti bẹ̀rù ẹ̀gàn ènìyàn tàbí bẹ̀rù àwọn ọ̀rọ̀ òdì wọn.16 Pẹ̀lú Olùgbàlà tí ó wà ní ipò àti àwọn wòlíì alààyè láti tọ́ wa sọ́nà, “tani ó lè lòdì sí wa?”17 Ẹ jẹ́ kí a ní ìgboyà, láìsí àforíjì, jẹ́ alágbára, má ṣe tijú, olóòótọ́, kí a má ṣe bẹ̀rù bí a ṣe ngbé ìmọ́lẹ̀ Olúwa dúró ní àwọn ọjọ́ ìkẹhìn wọ̀nyí.18

Olùgbàlà sọ kedere pé “ẹnikẹ́ni tí yìó bá jẹ́wọ́ mi níwájú ènìyàn, òun ni èmi ó jẹ́wọ́ níwájú Baba mi. … Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí yìó bá sẹ́mi mi níwájú ènìyàn, òun ni èmi ó sẹ níwájú Baba mi.”19

Nítorínáà, nígbàtí àwọn kan yíò fẹ́ràn Ọlọ́run tó nbọ̀ láìsí àwọn òfin, ẹ jẹ́ kí a fi ìgboyà jẹ́rìí nínú àwọn ọ̀rọ̀ Alàgbà D. Todd Christofferson pé “Ọlọ́run tí kò béèrè ohunkóhun jẹ́ Ọlọ́run tí kò sí.”20

Nígbàtí àwọn kan yíò fẹ́ láti yan àwọn òfin tí wọ́n ntẹ̀lé, ẹ jẹ́ kí a fi ayọ̀ gba ipè Olùgbàlà láti “gbé nípa gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu Ọlọ́run jáde.”21

Nígbàtí ọ̀pọ̀ gbàgbọ́ pé Olúwa àti Ìjọ Rẹ̀ gba ṣíṣe “ohunkóhun ti ọkàn [wa] fẹ́,”22 ẹ jẹ́ kí á tẹ̀síwájú nípa agbára láti kéde pé kò tọ́ láti “tẹ̀lé ogunlọ́gọ̀ láti ṣe ibi”23 nítorí “ọ̀pọ̀ ènìyàn kò lè ṣe àtúnṣe ohun tí Ọlọ́run ti kéde pé ó jẹ́ àṣìṣe.”24

“A! rántí, rántí… bí àwọn òfin Ọlọ́run ti le tó [síbẹ̀ títúsílẹ̀] ni àwọn òfin Ọlọ́run.”25 Kíkọ́ wọn lọ́nà tó ṣe kedere ni a lè rí nígbà míràn gẹ́gẹ́ bí ìṣe àìfaradà. Nítorínáà, ẹ jẹ́ ká fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ hàn pé kì í ṣe pé ó ṣeéṣe nìkan, ṣùgbọ́n ó ṣe pàtàkì láti nífẹ̀ẹ́ ọmọ Ọlọ́run tó bá gba àwọn ohun tó yàtọ̀ sí tiwa mọ́ra.

A lè gba láti bọ̀wọ̀ fún àwọn míràn láìsí ìfọwọ́sí àwọn ìgbàgbọ́ tàbí àwọn ìṣe wọn tí kò sí ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Olúwa. Kò sí ìwúlò láti rúbọ òtítọ́ lórí pẹpẹ ìtẹ́wọ́gbà àti fífẹ́ àwùjọ.

Síónì àti Bábílónì kò báramu. “Kò sí ẹnití ó lè sìn olúwa méjì.”26 Ẹ jẹ́ kí gbogbo wa rántí ìbéèrè tó nwọlé tọ Olùgbàlà, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi npè mí ní, Olúwa, Olúwa, tí ẹ̀yin kò sì ṣe àwọn ohun tí mo sọ?”27

Ẹ jẹ́ kí a fi ìfẹ́ wa sí Olúwa hàn nípasẹ̀ ìgbọràn àtọkànwá, àfínnúfíndọ̀ ṣe.

Tí ẹ bá nímọ̀lára pé ẹ wà láàrín ọmọlẹ̀hìn rẹ àti ayé, ẹ jọ̀wọ́ ẹ rántí pé Olùgbàlà olùfẹ́ni yín “ránṣẹ́ ìfipè kan … , nítorí a na apá àánú [fún yin], ó sì wípé: Ronúpíwàdà, Èmi ó sì gbà yín.”28

Ààrẹ Nelson kọ́ni pé “Jésù Krístì yio ṣe lára àwọn iṣẹ́ alágbára Rẹ̀ laarin ìsisìyí sí ìgbà tí Yìó padà wá lẹ́ẹ̀kansi.”29 Ṣùgbọ́n ó tún kọ́ni pé “àwọn tí ó bá yan ọ̀nà Olúwa yíò ṣeéṣe kí ó farada inúnibíni.”30 Níwọ̀n bí wọ́n ti “kà wọ́n yẹ láti jìyà ìtìjú nítorí orúkọ rẹ̀”31 lè jẹ́ ìpín tiwa nígbà míràn bí a ṣe “njẹ́ kí ohùn Rẹ̀ mú ipò àkọ́kọ́ ju èyíkéyìí míràn lọ.”32

“Alábùkúnfún ni òun,” Olùgbàlà wípé, “ẹnikẹ́ni tí a kò bínú nínú mi.”33 Níbòmíràn a kọ́ pé “àlàáfíà ńlá ní àwọn tí ó fẹ́ràn òfin rẹ: kò sì sí ohun tí yíò mú wọn bínú.”34 Kò sí! Nítorí náà, ẹ jẹ́ ká bi ara wa léèrè pé, “Ṣé mo nfaradà fún ìgbà díẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí ìpọ́njú tàbí inúnibíni bá dìde nítorí ọ̀rọ̀ náà, nípa èyí ṣé a nmú mi bínú?35 Ṣé mo fìdímúlẹ̀ gbọin gbọin lórí àpáta Jésù Krístì àti àwọn ìránṣẹ́ Rẹ̀?”

Àwọn ẹlẹ́mìí ìbálòpọ̀ npolongo pé òtítọ́ wulẹ̀ jẹ́ ìbákẹ́gbẹ́ ìkọ́lé, pé kò sí àwọn ìlànà ìwà rere. Ohun ti won nsọ lóòótọ́ ni pé kò sí ẹ̀ṣẹ̀,36 pé “ohunkóhun tí ènìyàn [ṣe] kì í ṣe ìwà ọ̀daràn,”37 ìmòye kan tí ọ̀tá nsọ pé ó jẹ́ òǹkọ̀wé ìgbéraga! Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a ṣọ́ra fún àwọn ìkookò tí wọ́n wọ aṣọ àgùntàn tí wọ́n máa ngbanisíṣẹ́ nígbà gbogbo tí wọ́n sì “[nlo ìfiyèsí] ọgbọ́n wọn lọ́pọ̀lọpọ̀ láti bo àwọn àbùkù ìwà [tiwọn].”36

Bí a bá fẹ́ jẹ́ àwọn akíkanjú ọmọẹ̀hìn Krístì, a ó rí ọ̀nà kan. Bíbẹ́ẹ̀kọ́, ọ̀tá náà nfúnni ní àwọn òmíràn tí ó wuni. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọẹ́hìn olótítọ́ “a kò gbọ́dọ̀ tọrọ àforíjì fún àwọn ohun tí a gbàgbọ́ tàbí kí a fà sẹ́hìn kúrò nínú ohun tí a mọ̀ pé ó jẹ́ òtítọ́.”39

Ní ìparí, ọ̀rọ̀ kan nípa àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run mẹẹdógún tíwọn joko lẹ́hìn mi. Nígbàtí àwọn ti ayé “wí fún àwon aríran pé, Ẹ máṣe ríran; àti fún àwọn wòlíì pé, “Ẹ máṣe sọtẹ́lẹ̀,”40 àwọn olóòótọ́ “ni a dé ní adé pẹ̀lú àwọn ìbùkún láti òkè, bẹ́ẹ̀ni, àti pẹ̀lú àwọn òfin tí kì í ṣe díẹ̀, àti pẹ̀lú àwọn ìfihàn ní àkókò wọn.”41

Kò yani lẹ́nu pé, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí sábà máa ndi ọ̀pá mànàmáná fún àwọn tí kò láyọ̀ sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí àwọn wòlíì ṣe kéde rẹ̀. Àwọn tí ó kọ àwọn wòlíì kò mọ̀ pé “kò sí àsọtẹ́lẹ̀ inú Ìwé Mímọ́ tí [yíò jẹ́] ti ìtumọ̀ àṣírí èyíkéyìí” tàbí àbájáde ìfẹ́ inú ènìyàn “ṣùgbọ́n [pé] àwọn ènìyàn mímọ́ Ọlọ́run [nsọ̀rọ̀ nísisìyí] bí a [ti] ndarí wọn nípasẹ̀ Ẹ̀mí mímọ́.”40

Bíi ti Páùlù, àwọn ènìyàn Ọlọ́run wọ̀nyí “kò … tijú ẹ̀rí Olúwa wa” wọ́n sì jẹ́“ [àwọn] ẹ̀lẹ́wọ̀n Rẹ̀”43 ní ọgbọ́n pé ẹ̀kọ́ tí wọ́n nkọ́ni kì í ṣe tiwọn bíkòṣe Tirẹ̀ ẹni tí ó pè wọ́n. Bíi ti Pétérù, wọn “kò lè ṣàì sọ ohun tí [wọ́n] ti rí, tí wọ́n sì ti gbọ́.”44 Mo jẹ́rìí pé Àjọ Ààrẹ Ìkínní àti Iyejú àwọn Méjìlá jẹ́ àwọn ènìyàn rere àti olódodo tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run àti àwọn ọmọ Rẹ̀, tí Óun sì nífẹ wọn. Ọ̀rọ̀ wọn ni kí a gbà bí ẹnipé láti ẹnu Olúwa “nínú gbogbo sùúrù àti ìgbàgbọ́. Nítorí nípa ṣíṣe àwọn ohun wọ̀nyí ìlẹ̀kùn ọ̀run àpáàdì kò ní borí [wa]; … Olúwa Ọlọ́run yíò sì tú agbára òkùnkùn kúrò níwájú [wa].”43

“Kò sí ọwọ́ àìmọ́ tí ó lè dá iṣẹ́ náà dúró láti tẹ̀síwájú”;46 yíò rìn lọ́nà ìṣẹ́gun pẹ̀lú tàbí láìsí ìwọ tàbí èmi, nítorínáà “Ẹ yan ẹni tí ẹ̀yin yíò sìn ní òní.”47 Ẹ máṣe jẹ́ kí á tàn tàbí kí á dẹ́rù bà yín nípasẹ̀ àwọn ariwo ọ̀tá tó njáde láti ilé nla àti gbígbòrò. Àwọn decibel àìnírètí wọn kò báramu fún ipa ìfọ̀kànbalẹ̀ ti ìdákẹ́jẹ́, ohùn kékeré lórí àwọn ìrora ọkàn àti àwọn ẹ̀mí ìròbìnújẹ́.

Mo jẹ́rìí pé Kristi wà láàyè, pé Òun ni Olùgbàlà àti Olùràpadà wa, àti pé Ó ndarí Ìjọ Rẹ̀ nípasẹ̀ Àjọ Ààrẹ Ìkínní àti Iyejú àwọn Àpọ́stélì Méjìlá, nípa bẹ́ẹ̀ ní ìdánilójú pé a kò “sọ wá síwá sẹ́hìn, tí a ngbé kiri pẹ̀lú gbogbo ẹ̀fúùfù ti ẹ̀kọ́.”48

“Àwọn ọmọẹ̀hìn Jésù Krístì tóótọ́,”Ààrẹ Nelson kọ́ni, “nfẹ́ láti yara wọn sọ́tọ̀, sọ̀rọ̀ síta, kí wọ́n sì yàtọ̀ sí àwọn ènìyàn ayé. Wọ́n jẹ́ akọni, olùfọkànsìn, àti onígboyà,”49

Ẹ̀yin arakùnrin àti arábìnrin, ó jẹ́ ọjọ́ rere kan láti jẹ́ rere! Ní orúkọ mímọ́ ti Jésù Krístì, àmín