Ìpàdé Àpapọ̀ Gbogbogbò
Òtítọ́ Ayérayé
Ìpàdé àpapọ̀ gbogbogbò Oṣù Kẹ́wàá 2023


Òtítọ́ Ayérayé

Ìnílò wa láti dá òtítọ́ mọ̀ kò tíì ṣe pàtàkì jù báyi lọ rí!

Ẹ̀yin Arákùnrin àti arábìrin, ẹ ṣeun fún ìfọkànsìn yín sí Ọlọ́run Baba àti sí Ọmọ Rẹ̀, Jésù Krístì, ẹ sì ṣeun fún ìfẹ́ àti iṣẹ̀ ìsìn yín sí ara yín. Ẹ jẹ́ àrà ọ̀tọ̀ nítòótọ́!

Ọ̀rọ̀-ìṣíwájú

Lẹ́hìn tí ìyàwó mi, Anne, àti èmi gba ìpè kan láti sìn bí olùdarí mísọ̀n ìgbà kíkún, ẹbí wa pinnu láti kọ́ orúkọ ìránṣẹ́ ìhìnrere kọ̀ọ̀kan kí a tó dé sí inú pápá. A gba àwọn fọ́tò, a ṣe àwọn káàdì pélébé, a sì bẹ̀rẹ̀sí ṣe àṣàrò àwọn ìwò ojú àti ṣíṣe àkọ́sórí àwọn orúkọ.

Nígbà tí a dé, a ṣe àwọn ìpàdé àpapọ̀ ọ̀rọ̀-ìṣíwájú pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́-ìhìnrere. Bí a ti ndarapọ̀, mo rọra gbọ́ ọmọkùnrin wa ẹni ọdún mẹ́sãn:

“Ó dára láti pàdé rẹ, Sámù!”

“Rákẹ́lì, níbo lo ti wá?”

Wáò, Dáfídì, o ga o!”

Pẹ̀lú àníyàn, mo lọ bá ọmọkùnrin wa mo sì sọ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́ pé, “Héè, jẹ́ ká rántí láti tọ́ka sí àwọn ìránṣẹ́-ìhìnrere bí Alàgbà tàbí Arábìnrin.”

Ó wò mí pẹ̀lú ìwò ojú dídàrú ó sì wí pé, “Baba, mo rò pé ó yẹ kí a ṣe àkọ́sórí àwọn orúkọwọn ni.” Ọmọkùnrin wa ṣe ohun tí ó rò pé ó tọ́ ní dídá lórí òye rẹ̀.

Nítorínáà, kínni òye wa nípa òtítọ́ nínú ayé òde òní? A nní àtakò léraléra pẹ̀lú àwọn èrò inú líle, ríròhìn pẹ̀lú ẹtanú, àti àkọsílẹ̀ tí kò pé. Ní àkókò kannáà, ìwọ̀n àti àwọn orísun àwọn ìwífúnni yi ngbilẹ̀ si. Ìnílò wa láti dá òtítọ́ mọ̀ kò tíì ṣe pàtàkì jù báyi lọ rí!

Òtítọ́ ṣe kókó fúnwa láti ṣe àgbékalẹ̀ kí a sì fún ìbáṣepọ̀ wa pẹ̀lú Ọlọ́run lókun, rí àlàáfíà àti ayọ̀, kí a sì dé ibi agbára àtọ̀runwá wa. Loni, ẹ jẹ́kí á gbé àwọn ìbéèrè wọ̀nyí yẹ̀ wò:

  • Kínni òtítọ́, àti kínni ìdí tí ó fi ṣe pàtàkì?

  • Báwo ni a ó ti rí òtítọ́?

  • Nígbàtí a bá rí òtítọ́, báwo ni a ti le ṣe àbápín rẹ̀?

Òtítọ́ Jẹ́ ti Ayérayé

Olúwa ti kọ́wa nínú ìwé-mímọ́ pé, “òtítọ́ ni ìmọ àwọn nkan bí wọ́n ṣe wà, àti bí wọ́n ṣe ti wà rí, àti bí wọn yíó ṣe wá” (Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 93:24). “A kò dá a tàbí ṣe é” (Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 93:29) àti pé “kò ní òpin” (Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 88:66).1 Òtítọ́ jẹ́ pípé, àìlèyẹ̀, àìleyípadà. Ní àwọn ọ̀rọ̀ míràn, òtítọ́ jẹ́ ti ayérayé.2

Òtítọ́ nràn wá lọ́wọ́ láti yẹra fún ẹ̀tàn,3 dá rere mọ̀ yàtọ̀ sí ibi,4 gba ààbò,5 àti láti rí ìtùnú àti ìwòsàn.6 Bákannáà òtítọ́ le ṣe atọ́nà àwọn ìṣe wa,7 sọ wá di òmìnira,8 yà wá sí ḿimọ́,9 kí ó sì darí wa sí ìyè ayérayé.10

Ọlọ́run Nfi Òtítọ́ Ayérayé Hàn

Ọlọ́run nfi òtítọ́ ayérayé hàn sí wa nípasẹ̀ àjọṣe àwọ̀n ìbáṣepọ̀ onífihàn kan tí ó ní Òun Fúnra Rẹ̀, Jésù Krístì, Ẹmí Mímọ́, àwọn wòlíì, àti àwa nínú. Ẹ jẹ́kí á sọ ìyàtọ́ síbẹ̀ ìfarakọ́ra àwọn ipa tí olùkópa kọ̀ọ̀kan nkó nínú ìlànà yí.

Àkọ́kọ́, Ọlọ́run ni orísun gbogbo òtítọ́ ayérayé náà.11 Òun àti Ọmọ Rẹ̀, Jésù Krístì,12 ní òye pípé ti òtítọ́ wọ́n sì nfi ìgbà gbogbo ṣe ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ àti àwọn òfin tòótọ́.13 Agbára yí nfún Wọn láàyè láti ṣe ẹ̀dá kí wọ́n sì ṣe àkóso àwọn ayé14 ati bákannáà láti fẹ́ràn, ṣe ìtọ́ni, ati láti ṣìkẹ́ ọ̀kọ̀ọ̀kan wa ní pípé,15 Wọ́n fẹ́ kí á ní òye kí a sì ṣe àmúlò òtítọ́ kí á le gbádùn àwọn ìbùkún náà bí Àwọn ti ṣe.16 Wọ́n le pín òtítọ́ bíi ènìyàn tàbí, ní wíwọ́pọ̀ síi, nípasẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ bí irú Ẹmí Mímọ́, àwọn ángẹ́lì, tàbí àwọn wòlíì alààyè.

Ìkejì, Ẹ̀mí Mímọ́ njẹri gbogbo òtítọ́.17 Òun nfi àwọn òtítọ́ hàn sí wa tààrà Ó sì njẹrí àwọn òtítọ́ tí a kọ́ni láti ọwọ́ àwọn míràn. Àwọn ìṣílétí láti ọ̀dọ̀ Ẹmí máa nsábà wá bíi àwọn èrò sí inú wa àti àwọn ìmọ̀lára sí ọkàn wa.18

Ìkẹta, àwọn wòlíì ngba òtítọ́ àti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọ́n sì npín òtítọ́ náà pẹ̀lú wa.10 A nkọ́ òtítọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì àtẹ̀hìnwá nínú àwọn ìwé mímọ́20 àti láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì alààyè ní ibi ìpàdé apapọ̀ gbogbogbò àti nípasẹ̀ àwọn ọ̀nà ìbáraẹni-sọ̀rọ̀ míràn tí a fọwọ́sí.

Ní iparí, ẹ̀yin àti èmi kó ipa pàtàkì nínú ìlànà yi. Ọlọ́run nretí wa láti lépa, dámọ̀, kí a sì mú òtítọ́ lò. Agbára wa láti gbà àti láti ṣe àmúlò òtítọ́ dá lórí okun ti ìbáṣepọ̀ wa pẹ̀lú Baba àti Ọmọ, ìdáhùnsí wa sí ipá ti Ẹmí Mímọ́, àti ìbárẹ́ wa pẹ̀lú àwọn wòlíì ti ọjọ́-ìkẹhìn.

A nílò láti rántí pé Sátánì nṣiṣẹ́ láti mú wa kúrò ninu òtítọ́. Ó mọ̀ pé láìsí òtítọ́, a kò le gba èrè ìyè ayérayé. Ó nhun àwọn fọ́nrán òtítọ́ pẹ̀lú àwọn ìmọ̀ orí ti ayé láti da iyè wa rú kí ó sì yọ wá lẹ́nu kúrò nínú ohun tí a bá wa sọ láti ọwọ́ Ọlọ́run.21

Lílépa, Dídámọ̀, àti Mímú Òtítọ́ Ayérayé Lò

Bí a ti nlépa òtítọ́ ayérayé,22 àwọn ìbéèrè méjì tó tẹ̀lé yí le rànwá lọ́wọ́ láti mọ̀ bóyá èrò inú kan wá láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run tàbí orísun míràn:

  • Njẹ́ èrò orí náà njẹ́ kíkọ́ni déédé nínú àwọn ìwé mímọ́ tàbí àwọn ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì alààyè bí?

  • Njẹ́ èrò orí náà ndi fífẹsẹ̀ múlẹ̀ nípa ẹ̀rí ti Ẹmí Mímọ́ bí?

Ọlọ́run nfi àwọn òtítọ́ ti ẹ̀kọ́ hàn nípasẹ̀ àwọn wòlíì, Ẹmí Mímọ́ sì nfi ẹsẹ̀ àwọn òtítọ́ náà múlẹ̀ Ó sì nràn wá lọ́wọ́ láti ṣe àmúlò wọn.23 A gbọ́dọ̀ lépa kí a sì múrasílẹ̀ láti gba àwọn ìṣílétí ti ẹ̀mí wọ̀nyí nígbàtí wọ́n bá wá.24 A jẹ́ olùgbà jùlọ sí ìjẹ́rí ti Ẹmí nígbàtí a bá jẹ́ onírẹ̀lẹ̀,25 tí a ngbàdúrà pẹ̀lú òtítọ́ ọkàn tí a sì nṣe àṣàrò àwọn ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,26 àti tí a npa àwọn òfin Rẹ̀ mọ́.27

Lẹ́hìn tí Ẹmí Mímọ́ bá ti fi ẹsẹ̀ òtítọ́ kan pàtó múlẹ̀ sí wa, òye wa njinlẹ̀ si bí a bá ti nfi ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ náà sínú ìṣe. Nígbàtí ó bá yá, bí a ti ngbé ìgbé ayé ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ náà, a njèrè ìmọ̀ kan tó dájú nípa òtítọ́ náà.28

Fún àpẹrẹ, mo ti ṣe àwọn àṣìṣe mo sì ní ìmọ̀lára ìrẹ̀wẹ̀sì fún àwọn yíyàn tí kò dára. Ṣùgbọ́n nípasẹ̀ àdúrà, àṣàrò, àti ìgbàgbọ́ nínú Jésù Krístì, mo gba ẹ̀rí nípa ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ ti ìrònúpìwàdà.29 Bí mo ti tẹ̀síwájú láti máa ronúpìwàdà, òye mi nípa ìrònúpìwàdà di lílágbára si. Mo ní ìmọ̀lára sísúnmọ́ Ọlọ́run àti Ọmọ Rẹ̀ si. Mo mọ̀ nísisìyí pé a lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì nípasẹ̀ Jésù Krístì, nítorípé mo ní ìrírí àwọn ìbùkún ti ìrònúpìwàdà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.30

Gbígbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run Nígbàtí Òtítọ́ Kò Tíì di Fífihàn Síbẹ̀

Nítorínáà, kínni a níláti ṣe nígbàtí a bá nfi tọkàntọkàn lépa fún òtítọ́ tí kò tíi` di fífihàn síbẹ̀? Mo ní ìyọ́nú fún àwọn wọnnì nínú wa tí wọ́n npòngbẹ fún àwọn ìdáhùn tí ó dàbí ẹnipé kò wá.

Sí Joseph Smith, Olúwa gbà á nímọ̀ràn pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ títí tí èmi yíò fi ri pé ó tọ́ láti sọ ohun gbogbo di mímọ̀ … nípa ohun náà.” (Ẹkọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 10:37).

Àti sí Emma Smith, Ó ṣe àlàyé pé, “Máṣe kùn nítorí àwọn ohun tí ìwọ kò tíì rí, nítorí a fi wọ́n pamọ́ fún ọ àti fún àwọn aráyé, èyítí ó jẹ́ ọgbọ́n nínú mi fún àkókò tí ó nbọ̀” (Ẹkọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 25:4)

Èmi pẹ̀lú ti wá àwọn ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè àtọkànwá. Ọpọ̀lọpọ̀ àwọn ìdáhùn ti wá; àwọn kan kò tíì wá.31 Bí a ti ndúró—ní gbígbẹ́kẹ̀lé ọgbọ́n àti ìfẹ́ Ọlọ́run, ní pípa àwọn òfin Rẹ̀ mọ́, àti fífi ara ti ohun tí a mọ̀—Òun nràn wá lọ́wọ́ láti rí àlàáfíà títí tí Òun ó fi fi òtítọ́ ohun gbogbo hàn.32

Níní Òye Ẹkọ́ àti Àwọn Ètò-ìmúlò

Nígbàtí a bá nwá òtítọ́, ó nrànwá lọ́wọ́ láti ní òye ìyàtọ̀ láàrin ẹ̀kọ́ àti ètò-ìmúlò. Ẹkọ́ ntọ́ka sí àwọn òtítọ́ ayérayé, bí irú àdánidá Ọlọ́run-olórí-ọ̀run, ètò ìgbàlà, ẹbọ ìṣètùtù ti Jésù Krístì, Ìlànà ni lílo ẹ̀kọ́ tó dá lórí àwọn ipò lọ́wọ́lọ́wọ́. Àwọn ìlànà nranwá lọ́wọ́ lati ṣe ìpínfúnni Ìjọ ní ọ̀nà tí ó létò.

Nígbàtí ẹ̀kọ́ kìí yípadà láé, ìlànà ndi títúnṣe láti àkókò dé àkókò. Olúwa nṣiṣẹ́ nípasẹ̀ àwọn wòlíì Rẹ̀ láti di ẹ̀kọ́ Rẹ̀ mú àti láti ṣe àtúnṣe sí àwọn ètò-ìmúlò Ìjọ ní ìbámu sí àwọn ìnílò àwọn ọmọ Rẹ̀.

Pẹ̀lú ẹ̀dùn, nígbàmíràn a máa nda ètò-ìmúlò pọ̀ pẹ̀lú ẹ̀kọ́. Bí a kò bá ní òye ìyàtọ̀ náà, a nfi ewu níní ìjákulẹ̀ ṣeré nígbàtí àwọn ètò-ìmúlò bá yípadà, àní a sì le bẹ̀rẹ̀ sí máa tọpinpin ọgbọ́n Ọlọ́run tàbí ipa onífihàn ti àwọn wòlíì,33

Kíkọ́ni ní Òtítọ́ Ayérayé

Nígbàtí a bá gba òtítọ́ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, Ó ngbàwá níyànjú láti ṣe àbápín ìmọ̀ náà pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn.34 A nṣe èyí nígbàtí a bá nkọ́ kíláàsì kan, ntọ́ ọmọ kan sọ́nà, tàbí ṣe àjọsọ àwọn òtítọ́ ìhìnrere pẹ̀lú ọ̀rẹ́ kan.

Ìfojúsùn wa ni láti kọ́ni ní òtítọ́ ní ọ̀nà tí yío pe agbára ìyílọ́kànpadà ti Ẹ̀mí Mímọ́.35 Ẹ jẹ́kí nṣe àbápín àwọn ìfipè kan tó rọrùn láti ọ̀dọ̀ Olúwa àti àwọn wòlíì Rẹ̀ tí ó le rànwá lọ́wọ́.36

  1. Dídá lé Bàbá Ọ̀run, Jésù Krístì, àti ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ Wọn.37

  2. Dúró dáradára nínú àwọn ìwé mímọ́ àti nínú àwọn ìkọ́ni àwọn wòlíì ọjọ́-ìkẹhìn.38

  3. Sinmi lé ẹ̀kọ́ tí a gbékalẹ̀ nípasẹ̀ ọ̀pọ̀ àwọn ẹlẹ́ri tì wọ́n ní àṣẹ.39

  4. Ẹ yẹra fún àdárò, àwọn èrò inú ti ara ẹni, tàbí àwọn èrò orí ti ayé.40

  5. Kọ́ni ní kókó ẹ̀kọ́ kan láàrin àkójọpọ̀ àwọn òtítọ́ ìhìnrere tó bárajọ.41

  6. Ẹ lo àwọn ètò ìkọ́ni tí ó npe ipá ti Ẹmí.42

  7. Ẹ ṣe ìbáraẹnisọ̀rọ̀ ní kedere láti yẹra fún èdè àìyédè.43

Sísọ Òtítọ́ nínú Ìfẹ́

Bí a ti nkọ́ni ní òtitọ́ ṣe pàtàkì gan-an Páùlù gbà wà níyànjú láti sọ “òtítọ́ nínú ìfẹ́” (wo Efésù 4:14–15). Èyí túmọ̀ sí pé òtítọ́ ní ààyè dídárajùlọ ti bíbùkún ẹlòmíràn nígbàtí a bá gbé e pẹ̀lú ìfẹ́ bíi-ti-Krístì.44

Òtítọ́ tí a bá kọ́ni láìsí ìfẹ́ le fa àwọn ìmọ̀lára ìdánilẹ́jọ́, ìrẹ̀wẹ̀sì, àti dídánìkanwà. Ó ṣaábà máa ndarí sí ìbínú àti ìpínyà—àní ìjà. Ní ọ̀nà míràn, ìfẹ́ láìsí òtítọ́ jẹ́ ṣíṣófo kò sì ní ìlérí ti dídàgbà.

Méjéèjì òtítọ́ àti ìfẹ́ ṣe kókó fún ìdàgbàsókè wa ti ẹ̀mí.45 Òtítọ́ npèsè ẹ̀kọ́, àwọn ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́, àti àwọn òfin tó ṣe dandan láti jèrè ìyè ayérayé, nígbàtí ìfẹ́ nṣe àmúwá ìwúrí tí a nílò láti ṣe ìgbàmọ́ra kí a sì ṣiṣẹ́ lórí ohun tí ó jẹ́ òtítọ́.

Mo fi ìmoore hàn títí láé fún àwọn ẹlòmíràn tí wọ́n fi sùúrù kọ́mi ní òtítọ́ ayérayé pẹ̀lú ìfẹ́.

Íparí

Ní ìparí, ẹ jẹ́kí nṣe àbápín àwọn òtítọ́ ayérayé tí wọ́n ti di ìdákọ̀ró sí ọkàn mi. Mo ti gba ìmọ̀ àwọn òtítọ́ wọ̀nyí nípa títẹ̀lé àwọn ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ tí a sọ̀rọ̀ lé lórí lóni.

Mo mọ̀ pé Ọlọ́run jẹ́ Baba wa Ọ̀run.46 Ó mọ ohun gbogbo,47 Ó ní gbogbo agbára,48 àti olùfẹ́ni ní pípé.49 Ó ṣe ẹ̀dá ètò kan tí ó mu ṣeéṣe fúnwa láti jèrè ìyè ayérayé kí a sì dàbí Rẹ̀.50

Bí apákan ètò náà, Ó rán Ọmọ Rẹ̀, Jésù Krístì, láti ràn wá lọ́wọ́.51 Jésù kọ́ wa láti ṣe ìfẹ́ Baba52 àti láti fẹ́ràn ara wa.53 Ó ṣe ètùtù fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa54 Ó sì fi ẹ̀mí Rẹ̀ lélẹ̀ ní orí àgbélèbú.55 Ó jí dìde kúrò nínú òkú lẹ́hìn ọjọ́ mẹ́ta,56 Nípasẹ̀ Krístì àti ore ọ̀fẹ́ Rẹ̀, a ó jínde,57 a le jẹ́ dídáríjì,58 a sì le rí okun nínú ìpọ́njú.59

Ní ìgbà iṣẹ́ ìránṣẹ́ Rẹ̀ ní ilẹ̀ ayé, Jésù gbé Ìjọ Rẹ̀ kalẹ̀.60 Lẹ́hìn àkókò díẹ̀, Ìjọ náà di yíyípadà, àwọn òtítọ́ sì sọnù.61 Jésù Krístì mú Ìjọ Rẹ̀ àti àwọn òtítọ́ ìhìnrere padàbọ̀sípò nípasẹ̀ Wòlíì Joseph Smith.62 Àti lóní, Krístì tẹ̀síwájú láti darí Ìjọ Rẹ̀ nípasẹ̀ àwọn wòlíì àti àwọn àpóstélì alààyè.63

Mo mọ̀ pé bí a ti nwá sí ọ̀dọ̀ Krístì, a le “sọ wá di pípé nínú rẹ̀” nígbẹ̀hìn (Mórónì 10:32), a le gba “ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ayọ̀ kan” (Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 93:33), kí a sì gba “gbogbo ohun tí Baba [náà] ní” (Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 84:38). Sí àwọn òtíiọ́ ayérayé wọ̀nyí ni mo jẹ́ ẹ̀rí ni orúkọ mímọ́ Jésù Krístì, àmín.

Àwọn Àkọsílẹ̀ ráńpẹ́

  1. Bákannáà wo Orin Dáfídì117:2; Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 1:39.

  2. “Ní ìlòdì sí àwọn ìyèméjì ti àwọn kan, irú nkan nítòótọ́ bíi títọ́ àti àṣìṣe. Nkan nítòótọ́ tí ó jẹ́ òtítọ́ pípé—òtítọ́ ayérayé. Ọ̀kan nínú àwọn àjàkálẹ̀ àrùn ti ìgbà tiwa ni pé àwọn ènìyàn tó kéré púpọ̀ ní iye ni wọ́n mọ ibití wọ́n le yà sí fún òtítọ́” (Russell M. Nelson, “Òtítọ́ Àìlábàwọ́n, Ẹkọ́ Àìlábàwọ́n, àti Ìfihàn Àìlábàwọ́n,” LiahonaNov. 2021, 6).

  3. Wo Joseph Smith—Matteu 1:37.

  4. Wo Mórónì 7:19.

  5. Wo 2 Nefì 1:9; Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 17:8.

  6. Wo Jákọ́bù 2:8.

  7. Wo Orin Dáfídì 119:105; 2 Néfì 32:3.

  8. Wo Jòhánnù 8:32; Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 98:8.

  9. Wo Jòhánù 17:17.

  10. Wo 2 Néfì 31:20.

  11. Wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 88:11-13; 93:36.

  12. Wo Jóhánnù 5:19–20; 7:16; 8:26; 18:37; Mósè 1:6.

  13. Wo Álmà 42:12–26; Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 88:41.

  14. Wo Mósè 1:30–39.

  15. Wo 2 Néfì 26:24.

  16. Wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 82:8-9.

  17. Wo Jòhánnù 16:13; Jákọ́bù 4:13; Moroni 10:5; Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 50:14; 75:10; 76:12; 91:4; 124:97.

  18. Wo Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 6:22–23; 8:2–3.

  19. Wo Jeremíàh 1:5, 7; Ámósì 3:7; Máttéù 28:16–20; Mórónì 7:31; Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 1:38; 21:4–6; 43:1–7. Wòlíì jẹ́ “ẹnì kan tí a ti pè nípa tí ó sì nsọ̀rọ̀ fún Ọlọ́run. Bíi ìrànṣẹ́ Ọlọ́run, wòlíì ngba àwọn òfin, àwọn àsọtẹ́lẹ̀, àti àwọn ìfihàn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run. Ojúṣe rẹ̀ ni láti mú ìfẹ́ àti ìhùwàsí Ọlọ́run ní tòótọ́ di mímọ̀ sí àwọn ẹ̀dá ènìyàn àti láti ṣe àfihàn ìtumọ̀ àwọn ìbáṣepọ̀ Rẹ̀ pẹ̀lú wọn. Wòlíì nkọ ẹ̀ṣẹ̀ sílẹ̀ ó sì máa nsọ ṣaájú nípa àwọn àyọrísí rẹ̀. Òun jẹ́ oníwàásù ti ìṣòdodo. Nígbàmíràn, àwọn wòlíì lè ní ìmísí láti sọ ṣaájú nípa ọjọ́-ọ̀la fún èrè ẹ̀dá ènìyàn. Bíótilẹ̀ríbẹ́ẹ̀, pàtàkì ojúṣe rẹ̀ ni láti jẹ́rí nípa Krístì. Ààrẹ̀ Ìjọ Jésù Krístì ti Àwọn Ènìyàn Mímọ́ Ọjọ́-ìkẹhìn jẹ́ wòlíì ti Ọlọ́run ní orí ilẹ̀ ayé lóni. Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Àjọ Ààrẹ Kínní àti àwọn Àpóstélì Méjìlá ní a múdúró bíi àwọn wòlíì, aríran, àti olùfihàn” (Atọ́nà sí Àwọn Ìwé Mímọ́, “Wòlíì,” Ibi Ìkàwé Ìhìnrere). Àpẹrẹ àwọn ìlànà ẹ̀kọ́ wọ̀nyí ni a rí nínú ìgbé ayé Ádámù (wo Moses 6:51–62), Ẹnọ́kù (wo Moses 6:26–36), Nóà (wo Moses 8:19, 23–24), Abráhámù (wo Gẹ́nẹ́sísì 12:1–3; Abráhámù 2:8–9), Mósè (wo Ẹksódù 3:1–15; Mósè 1:1–6, 25–26), Pétérù (wo Matteu 16:13–19), àti Joseph Smith (wo Ẹ̀kọ́ ati awọn Májẹ̀mú 5:6–10; 20:2; 21:4–6).

  20. Wo 2 Tímótéù 3:16.

  21. Wo Jòhánnù 8:44; 2 Néfì 2:18; Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 93:39; Mósè 4:4.

  22. Wo 1 Néfì 10:19. Ààrẹ Dallin H. Oaks kọ́ni pé: “A nílò láti ṣọ́ra bí a ti nlépa òtítọ́ [ti Ọlọ́run] tí a sì nyàn àwọn orísun fún ìwádìí náà. A kò níláti ronú òkìkí tàbí àṣẹ ti ayé bíi àwọn orísun tó péye. … Nígbàtí a bá lépa òtítọ́ nípa ẹ̀sìn, a níláti lo àwọn ètò ti ẹ̀mí tó yẹ fún ìwádìí náà: àdúrà, ẹ̀rí ti Ẹmí Mímọ́, àti àṣàrò ti àwọn ìwé mímọ́ àti ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì òde òní” (“Òtítọ́ àti Ètò náà,” Lìàhónà, Oṣù Kọkànlá 2018, 25).

  23. Alàgbà D. Todd Christofferson kọ́ni pé: “Àwọn Àpóstélì àti àwọn wòlíì … kéde ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ní àfikún, a gbàgbọ́ pé àwọn ọkùnrin àti obìnrin ní gbogbogbò àti àwọn ọmọdé pàápàá le kọ́ ẹ̀kọ́ láti ọ̀dọ̀, kí wọn ó sì jẹ́ títọ́ nípasẹ̀, ìmísí àtọ̀runwá ní ìdáhùn sí àdúrà àti àṣàrò ti àwọn ìwé mímọ́. … Àwọn ọmọ Ìjọ Jésù Krístì ni a fún ní ẹ̀bùn Ẹmí Mímọ́ náà, èyítí yíó ṣe àmúwá ìbáraẹnisọ̀rọ̀ tí ó ntẹ̀síwájú pẹ̀lú Baba wọn Ọ̀run. … Èyí kìí ṣe láti sọ pé olukúlùkù ọmọ ijọ nsọ̀rọ̀ fún Ìjọ tàbí le ṣe ìtumọ̀ àwọn ẹ̀kọ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n pé olukúlùkù le gba ìtọ́ni àtọ̀runwá ní kíkojú pẹ̀lú àwọn ìdojúkọ àti àwọn ànfààní ti ayé rẹ̀ lọ́kùnrin tàbí lóbìnrin” (“Ẹ̀kọ́ Krístì Náà,” Liàhónà, Oṣù Karun 2012, 89–90, note 2).

  24. Wo 2 Néfì 33:1–2.

  25. Wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 1:28.

  26. Wo Mórónì 10:3–5; Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 9:7–9; 84:85.

  27. Wo Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 5:35; 63:23; 93:27–28. Láìka àwọn áapọn onítara wa sí, àwọn kan lára wa le máa tiraka síbẹ̀ láti ní ìmọ̀lára Ẹ̀mí nítorí àwọn ìpèníja ìlera ọpọlọ. Ìrẹ̀wẹ̀sì, àníyàn, ati awọn ipò miràn le ṣe àfikún ìrújú sí síṣe ìdámọ̀ Ẹmí Mímọ́. Ní irú àwọn àkókò bẹ́ẹ̀, Olúwa npè wá láti tẹ̀síwájú ní gbígbé ìgbé ayé ìhìnrere, Òun ó sì bùkún wa (wo Mosiah 2:41). A le wò fún àfikún àwọn nkan síṣe—bí fífetísí orin mímọ́, kíkópa nínú iṣẹ́-ìsìn, tàbí lílo àkókò nínú àdánidá—tí ó nràn wá lọ́wọ́ láti ní ìmọ̀lára àwọn èso ti Ẹ̀mí (wo Galátíà 5:22–23) tí ó sì nfi okun fún àsopọ̀ wa sí Ọlọ́run.

    Alàgbà Jeffrey R. Holland sọ̀rọ̀ pé: “Nígbànáà báwo ni o ti le dáhùn dára jùlọ nígbàtí àwọn ìpèníjà ti ọpọlọ tàbí ẹ̀dùn ọkàn bá dojúkọ ìwọ tàbí àwọn tí o fẹ́ràn? Ju gbogbo rẹ̀ lọ, máṣe sọ ìgbàgbọ́ nù ninú Baba rẹ ní Ọ̀run, ẹnití ó fẹ́ràn rẹ ju bí ìwọ ti le ní òye lọ. … Fi pẹ̀lú ìgbàgbọ́ lépa àwọn ìṣe ìsìn tí àkókò ti dán wò tí ó máa nmú Ẹmí Olúwa wá sínú aye yín. Ẹ máa wá ìmọ̀ràn ti àwọn tí wọ́n mú àwọn kọ́kọ́rọ́ lọ́wọ́ fun ìwà-lálàáfíà yín. Béèrè fún kí o sì mọ iyì àwọn ìbùkún oyè-àlùfáà. Gba ounjẹ Olúwa ní ọ̀sẹ̀-ọ̀sẹ̀, kí o sì mú ṣinṣin sí àwọn ìlérí tó nsọni di pípé ti Ètùtù Jésù Krístì. Gbàgbọ́ nínú àwọn iṣẹ́ ìyanu. Mo ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn tó wá nígbàtí gbogbo àwọn ìtọ́kasí miràn sọ pé ìrètí ti sọnù. Ìrètí kò sọnù láéláé” (“Bí Ohun-èlò Fífọ́,” Liahona, Nov. 2013, 40–41).

  28. Wo Jòhánù 7:17; Álmà 32:26–34. Ní ìgbẹ̀hìn, Ọlọ́run fẹ́ fúnwa láti jèrè òtítọ́ “ẹsẹ lórí ẹsẹ, ìkọ́ni lé ìkọ́ni,” títí a ó fi ní òye ohun gbogbo (wo Òwe 28:5; 2 Néfì 28:30; Ẹ̀kọ́ Àti Àwọn Májẹ̀mú 88:67; 93:28).

  29. Wo 1 Jòhánù 1:9-10; 2:1–2.

  30. Ààrẹ Russell M. Nelson ṣe àlàyé pé: “Kò sí ohunkóhun tó ntúnisílẹ̀ si, níyì si, tàbí ṣe pàtàkì sí ìlọsíwájú ẹnìkọ̀ọ̀kan wa ju ìfojúsùn déédé, ti ojoojúmọ́ lórí ìrònúpìwàdà. Ìronúpìwàdà kìí ṣe ìṣẹ̀lẹ̀ kan; ó jẹ́ ètò kan. Ó jẹ́ kọ́kọ́rọ́ sí ìdùnnú àti àláfíà ọkàn. Nígbàtí a bá fikún ìgbàgbọ́, ìrònúpìwàdà nṣí ààyè wa sí agbára Ètùtù ti Jésù Krístì” (“A Lè Ṣe Dáradára Síi Kí A Sì Di Dáradára Síi,” Lìàhónà, Oṣù Karũn 2019, 67).

  31. Èmi kò mọ gbogbo ìdí tí Ọlọ́run fi fa àwọn òtítọ́ ayérayé díẹ̀ sẹ́hìn kúrò lọ́dọ̀ wa, ṣùgbọ́n Alàgbà Orson F. Whitney pèsè ìwòye ìwúrí kan: “Ó jẹ́ ìbùkún láti gbàgbọ́ láì rí, níwọ̀nbí nípa lílo ìgbàgbọ́ ni ìdàgbàsókè ti ẹ̀mí ti nwá, ọ̀kan lára àwọn ohun nlá ti wíwà ènìyàn ní ìlẹ̀ ayé; nígbàtí ìmọ̀, nípa gbígbé ìgbàgbọ́ mì, ndènà lílo rẹ̀, nípa báyí nṣe ìdíwọ́ fún ìdàgbàsókè náà. ‘Ìmọ̀ jẹ́ agbára’; ohun gbogbo yío sì di mímọ̀ ní àkókò tó yẹ. Ṣùgbọ́n ìmọ̀ tí kò gbó—mímọ̀ ní àkókò tí kò tọ́—jẹ́ ìjànbá sí ìlọsíwájú àti sí ìdùnnú” (“Jíjẹ́ Ti Ọrun Jésù Krístì,” Improvement Era, Jan. 1926, 222; bákannáà wo Lìàhónà, Oṣù Kejìlá 2003).

  32. Wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 76:5–10. Oluwa ṣe gba Hyrum Smith nímọ̀ràn bákannáà láti “máṣe wá láti kéde ọ̀rọ̀ mi, ṣùgbọ́n kọ́kọ́ wá láti gba ọ̀rọ̀ mi. … Pa ẹnu rẹ mọ́ kí o [sì] ṣe àṣàrò ọ̀rọ̀ mi” (Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 11:21–22). Wòlíì Álmà pèsè àpẹrẹ kan fún ṣiṣe lóri àwọn ìbéèrè tí kò tíì ní ìdáhùn: “Àwọn ohun ìjìnlẹ̀ wọ̀nyí ni a kò tĩ sọ di mímọ̀ fún mi ní kíkún; nítorínã èmi yíò dánu dúró” (Álmà 37:11). Ó ṣàlàyé bákannáà fún ọmọ rẹ̀ Corianton pé “ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ohun ìjìnlẹ̀ ló wà èyítí a fi pamọ́, tí ẹnìkẹ́ni kò mọ̀ wọ́n bíkòṣe Ọlọ́run fúnrarẹ̀” (Álmà 40:3). Bákannáà mo ti rí okun láti inú ìdáhùn Néfì nígbàtí a kojú rẹ̀ pẹ̀lú ìbéèrè kan tí òun kò le dáhùn: “Mo mọ̀ pé [Ọlọ́run] fẹ́ràn àwọn ọmọ rẹ̀; bíótilẹ̀ríbẹ̃, èmi kò mọ́ ìtúmọ̀ ohun gbogbo” (1 Néfì 11:17).

  33. Ní àfijọ, àwọn àṣà ìṣe kìí ṣe ẹ̀kọ́ tàbí ìlànà. Wọ́n le wúlò bí wọ́n bá rànwá lọ́wọ́ láti tẹ̀lé ẹ̀kọ́ àti ìlànà, ṣùgbọ́n bákannáà wọ́n le dènà dídàgbà wa ní ti ẹ̀mí bí wọn kò bá dá lórí àwọn ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ tòótọ́. A níláti yẹra fún àwọn àṣà tí kò mú ìgbàgbọ́ wa ninu Jésù Krístì dàgbà tàbí rànwá lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú sí ìhà ìyè ayérayé.

  34. Wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 15:5; 88:77–78.

  35. Wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 50:21–23.

  36. A mú un jáde láti inú ìwé “Àwọn Ìpilẹ̀sẹ̀ Ẹkọ́ fún Àrídájú Àìlábáwọn ti Ẹkọ́,” tí a fọwọ́sí nípasẹ̀ Ajọ Ààrẹ Ìkínní àti Iyejú àwọn Àpọ́stélì Méjìlá ní Oṣù Kejì 2023.

  37. Wo 1 Néfì 15:14. Olúwa darí àwọn ìránṣẹ́ Rẹ̀ láti yẹra fún fífi ojú sùn sórí àwọn ìjìnlẹ̀ ẹ̀kọ́, tàbí àwọn èrò inú, tí wọn kò ṣe pàtàkì sí ìhìnrere Rẹ̀: “Àti pé nípa àwọn ìjìnlẹ̀ ẹ̀kọ́ ni ìwọ kí yíò sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ yío kéde ironúpìwàdà àti ìgbàgbọ́ nínú Olùgbàlà, àti ìmúkúrò àwọn ẹ̀ṣẹ̀ nípa ìrìbọmi, àti nípa iná, bẹ́ẹ̀ni, àní Ẹ̀mí Mímọ́ náà” (Ẹ̀kọ́ Àti Àwọn Májẹ̀mú 19:31).

    Alàgbà Neil L. Andersen ṣe àlàyé pé: “Ẹ jẹ́ kí a fi ojú sun sórí Olùgbàlà Jésù Krístì àti ẹ̀bùn ètùtù ìrúbọ Rẹ̀. Èyí kò túmọ̀sí pé a kò lè sọ ìrírí kan láti inú ayé ti ara wa tàbí ṣe àbápín èrò kan láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹlòmíràn. Nígbàtí ẹ̀kọ́ wa lè jẹ́ nípa àwọn ẹbí tàbí iṣẹ́-ìsìn tàbí tẹ́mpìlì tàbí míṣọ̀n àìpẹ́, ohun gbogbo … gbọ́dọ̀ tọ́ka sí Olúwa Jésù Krístì“ (“A nsọ̀rọ̀ nípa Krìstì,” Làìhónà, Oṣù Kọkànlá 2020, 89–90).

  38. Wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 28:2–3, 8. Wòlíì Álmà gba àwọn tí a yàn nímọ̀ràn láti wàásù ìhìnrere láti “máṣe kọ́ni ní ohunkóhun bíkòṣe àwọn ohun èyítí òun ti kọ́ni, àti èyítí a ti sọ lati ẹnu àwọn wòlĩ mímọ́” (Mòsíàh 18:19).

    Ààrẹ Henry B/ Eyring sọ pé, “A gbọ́dọ̀ kọ́ni ní àwọn ẹ̀kọ́ pàtàkì ti Ìjọ bí ó ti wà nínú àwọn ìwé mímọ́ àti àwọn ìkọ́ni ti àwọn wòlíì, ojúṣe àwọn ẹnití ó jẹ́ láti kéde ẹ̀kọ́” (“Olúwa Yío Mú Ìkórè Pọ̀ Síi” [ìrọ̀lẹ́ pẹ̀lú Aláṣẹ Gbogbogbò, 6 Oṣù Kejì, 1998], nínú Teaching Seminary: Preservice Readings [2004], 96).

    Alàgbà D. Todd Christofferson jẹ́rìí pé “nínú Ìjọ lóni, gẹ́gẹ́bíi ti ìgbà àtijọ́, ṣíṣe àgbékalẹ̀ ẹ̀kọ́ ti Krístì tàbí síṣe àtúnṣe sí àwọn yíyà kúrò nínú ẹ̀kọ́ jẹ́ ọ̀ràn ìfihàn àtọ̀runwá sí àwọn tí Olúwa bùkún pẹ̀lú àṣẹ ti àpóstẹ́lì” (“Ẹkọ́ ti Krístì,” 86).

  39. Wo 2 Kọ́ríntì 13:1; 2 Néfì 11:3; Ethà 5:4; Ẹ̀kọ́ Àti Àwọn Májẹ̀mú 6:28. Alàgbà Neil L. Andersen ṣe àkíyèsí pé: “àwọn díẹ̀ kan máa nṣiyèmejì ìgbàgbọ́ wọn nígbàtí wọ́n bá rí ọ̀rọ̀ tí olùdarí Ìjọ kan sọ ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́hìn tí ó dàbí àìdọ́gba pẹ̀lú ẹ̀kọ́ wa. Ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ pàtàkì kan wà tó nṣe àkóso ẹ̀kọ́ Ìjọ. Ẹ̀kọ́ náà ni a kọ́ni nípasẹ̀ gbogbo ọmọ ẹgbẹ́ mẹ́ẹ̀dógún ti Àjọ Àarẹ Ìkínní àti Iyejú àwọn Méjìlá. Kò jẹ́ pípamọ́ sínú kọ̀rọ̀ abala ti ìpín-ọ̀rọ̀ kan. Àwọn ìpìlẹsẹ̀ ẹ̀kọ́ tòótọ́ ni a nkọ́ni léraléra àti nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn. Ẹkọ́ wa kò ṣòro láti rí” (“Àdánwò Ìgbàgbọ́ Yín,” Làìhónà, Oṣù Kọkànlá 2012, 41).

    Alàgbà Christofferson ní ìfarajọ kọ́ni pé: “Ó nílati jẹ́ rírántí pé kìí ṣe gbogbo gbólóhùn-ọ̀rọ̀ tí a sọ nípasẹ̀ olórí Ìjọ kan, ti àtẹ̀hìnwá tàbí ti lọ́wọ́lọ́wọ́, ló jẹ́ ẹ̀kọ́ ní dandan. Ó jẹ́ ìmọ̀ tí ó wọ́pọ̀ nínú Ìjọ pé gbólóhùn-ọ̀rọ̀ tí olùdarí kan bá sọ ní ìgbà kan ṣoṣo ṣaábà máa ndúró fún èrò inú ti araẹni, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti jẹ́ rírò dáadáa, tí kò túmọ̀ sí jíjẹ́ àfọwọ́sí tàbí ti abẹ́ òfin fún gbogbo Ìjọ” (“Ẹkọ́ ti Krístì,” 88).

  40. Wo 3 Néfì 11:32, 40 Ààrẹ Gordon B. Hinckley wí pé: “Mo ti sọ̀rọ̀ tẹ́lẹ̀ nípa pàtàkì pípa ẹ̀kọ́ Ìjọ mọ́ ní àìléèrí. … Mo ní ìdààmú nípa èyí Àwọn àìdára kékèké nínú ìkọ́ni ti ẹ̀kọ́ le dárí sí àwọn àìṣòtítọ́ nlá àti ibi” (Àwọn ìkọ́ni ti Gordon B. Hinckley [1997], 620).

    Ààrẹ Dallin H. Oaks kìlọ̀ pé àwọn kan wà “tí wọ́n nyàn àwọn gbólóhùn díẹ̀ kan láti inú àwọn ìkọ́ni ti wòlíì kan tí wọn á sì lo ìwọ̀nyí láti ṣe àtìlẹhìn fún ètò òṣelú wọn tàbí àwọn èrèdí miràn ti ara ẹni. … Láti jèrè àwọn ọ̀rọ̀ wòlíì kan láti ṣe àtilẹ́hìn fún ètò ti ara ẹni, ti òṣèlú tàbí ìṣúná tàbí bẹ́ẹ̀kọ́, jẹ́ láti gbìyànjú láti fi ọwọ́ rọ́ wòlíìnáà sẹ́hìn, kìí ṣe láti tẹ̀lé òun” (“Áwọn Okun Wa Le Di Ìṣubú Wa” [Brigham Young University devotional, Oṣù Kẹfà 7, 1992], 7, speeches.byu.edu).

    Ààrẹ Henry B. Eyring kìlọ̀ pé: “Ẹkọ́ njèrè agbára rẹ̀ bí Ẹ̀mí Mímọ́ tí nfẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ pé ó jẹ́ òtítọ́. … Nítorípé a nílò Ẹmí Mímọ́, a gbọdọ̀ ní ìfura kí a sì ṣọ́ra láti máṣe lọ tayọ kíkọ́ni ní ẹ̀kọ́ òtítọ́. Ẹmí Mímọ́ jẹ́ Ẹmí ti Òtítọ́. Ìfẹsẹ̀múlẹ̀ rẹ̀ ni a npè nípa yíyẹra wa fún àhesọ tàbí ìtùmọ̀-ọ̀rọ̀ ti ara ẹni. Èyí le ṣòro láti ṣe. … Ó máa njẹ́ ìdánniwò láti gbìyànjú ohun titun tàbí wíwuni kan. Ṣùgbọ́n a npe Ẹmí Mímọ́ bíi alábàárìn wa nígbàtí a bá ṣọ́ra latí kọ́ni ní ẹ̀kọ́ òtítọ́ nìkan. Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀nà tí ó dájú jùlọ láti yẹra fún àní dídé ìtòsí ẹ̀kọ́ èké ni láti yàn láti jẹ́ ìwọ̀ntúnwọ̀nsì nínú ìkọ́ni wa. A njèrè ààbò nípa jíjẹ́ ìwọ̀ntúnwọ̀nsì, kékeré sì nsọnù” (“The Power of Teaching Doctrine,” Liahona, July 1999, 86).

    Alàgbà Dale G. Renlund kọ́ni pé: “Wíwá òyè títóbijù jẹ́ apákan pàtàkì ti ìdàgbàsókè wa ti-ẹ̀mí, ṣùgbọ́n ẹ jọ̀wọ́ ẹ fura. Èrèdí kò lè rọ́pò ìfihàn. Lílérò kò ní darí lọ sí ìmọ̀ títóbijù ti-ẹ̀mí, ṣùgbọ́n ó lè darí wa lọ sí ẹ̀tàn tàbí yí ìfojúsùn wa kúrò ní ohun tí ó ti di fífihàn” (“Àdánidá Àtọrunwá Yín àti Àyànmọ́ Ayérayé,” Làìhónà, Oṣù Karun 2022, 70).

  41. Wo Máttéù 23:23 Ààrẹ Joseph F. Smith kìlọ pé: “Ó jẹ̀ ohun tí kò mú ọgbọ́n wa rárá láti mú abala òtítọ́ kan kí a sì kà á sí bí ẹnipé ó jẹ̀ gbogbo nkan náà. … Gbogbo àwọn ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ tí a fihàn nípa ìhìnrere Krístì ṣe dandan àti kókó nínú ètò ìgbàlà.” Ó ṣàlàyé síwájú pé: “Kìí ṣe ìlànà rere tàbí ẹ̀kọ́ tí ó múná láti mú ìkan nínú ìwọ̀nyí, kì a yà á sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo ètò nipa òtítọ́ ìhìnrere, kí a sọ ọ́ di ààyò pàtàkì, kì a sì gbé ara lé e fún ìgbàlà àti ìtẹ̀síwájú wa. … Gbogbo wọn ṣe dandan” (Ẹ̀kọ́ Ìhìnrere, 5th ed. [1939], 122).

    Alàgbà Neal A. Maxwell ṣàlàyé pé: “Àwọn ìpilẹ̀sẹ̀ ẹ̀kọ́ ti ìhìnrere … nílò ìbárajọ. Nígbàtí a bá fà wọn jìnnà sí ara wọn tàbí yà wọ́n sọ́tọ̀, àwọn ìtumọ̀ àti ìmúlò ti àwọn ẹ̀kọ́ wọ̀nyí ní ti ènìyàn le di àìlétò. Ìfẹ́, bí a kò bá yẹ̀ ẹ́ wò nípa òfin keje, le di ti ara. Àtẹnumọ́ ti òfin karun tí ó yẹ fún ìyìn lórí bíbu ọlá fún àwọn òbí, bíkòṣepé a yẹ̀ ẹ́ wò nípa òfin kinní, le yọrí sí ìfarasìn àìnídi sí àwọn òbí lásán dípò sí Ọlọ́run. … Àní sũrù ni a le mú dọgba nípa ‘bíbáwí ní àkókò pẹ̀lú ìyára, nígbàtí a bá ní ìmísí nípasẹ̀ Ẹ̀mí Mímọ́’ [Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 121:43]” (“Ẹ kíyèsi, àwọn Ọ̀tá Parapọ̀,” Ensign, May 1993, 78–79).

    Ààrẹ Marion G. Romney ṣàlàyé pé, “Wíwá inú [àwọn ìwé mímọ́] fún èrèdí láti ṣe àwárí ohun tí wọ́n kọ́ni bí Jésù ti rọ̀ wá jẹ́ igbe tí ó jìnǹa sí wíwá inú wọn fún èrèdí ti rírí àwọn ẹsẹ tí a le tẹ̀ sí lílò láti ṣe àtìlẹ́hìn fún ìparí kan tí a ti ní lọ́kàn” (“Àwọn Àkọsílẹ̀ Oníye Nlá,” Ensign, Oṣù Kẹsan 1980, 3).

  42. Wo 2 Néfì 2:8Moroni 6:4 Alàgbà Jeffrey R. Holland tẹnumọ́ ìnílò láti bára ẹni sọ̀rọ̀ ìhìnrere Jésù Krístì ní ọ̀nà kan tó ndarí sí ìgbéga ti ẹ̀mí nípasẹ̀ agbára Ẹ̀mí Mímọ́: “Olúwa kò tíì fi ìmọ̀ràn pẹ̀lú àtẹnumọ́ tóbẹ́ẹ̀ fún Ìjọ rí láé ju pé a níláti kọ́ni ní ìhìnrere ‘nípasẹ̀ Ẹ̀mí, àní Olùtùnú náà tí a rán jáde láti kọ́ni ní òtítọ́.’ Njẹ́ a nkọ́ni ní ìhìnrere ‘nípasẹ̀ Ẹmí òtítọ́?’ Ó ti ṣe ìbéèrè: Tàbí njẹ́ a nfi kọ́ni ‘ní àwọn ọ̀nà míràn bí? Àti bí ó bá sì jẹ́ nípa àwọn ọ̀nà míràn,’ Ó kìlọ̀, ‘kìí ṣe ti Ọlọ́run’ [Ẹkọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 50:14, 17–18]. … Kò sí ìkẹ́kọ̀ọ́ ti ayérayé tí ó le ṣẹlẹ̀ láì sí ìtanijí ti Ẹ̀mí lati ọ̀run. … Èyí ni ohun tí àwọn ọmọ ijọ wa fẹ́ gan-an. … Wọ́n fẹ́ kí ìgbàgbọ́ wọn jẹ́ síṣe odi fún àti ìrètí wọn ní sísọ di ọ̀tun. Wọ́n fẹ́, ní kúkúrú, láti jẹ́ bíbọ́ nípa ọ̀rọ̀ rere Ọlọ́run, láti jẹ́ fífún lókun nípa àwọn agbára ọ̀run” (“Olùkọ́ni Máa Nwá láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run,” Ensign, Oṣù Karũn 1998, 26).

  43. Wo Álmà 13:23 Ní sísọ̀rọ̀ nípa Baba wa Ọ̀run, Ààrẹ Russell M. Nelson jẹ́ri pé, “Ó nbani sọ̀rọ̀ ní ìrọ̀rùn, jẹ́jẹ́, àti pẹ̀lú ṣìṣe kedere tóbẹ́ẹ̀ tí a kò le ṣì Í gbọ́” (“Ẹ Máa Gbọ́ Tirẹ̀,” LLàìhónà, Oṣù Karun 2020, 89).

  44. Wo Orin Dáfídì 26:3; Rómù 13:10; 1 Kọ́rintì 13:1–8; 1 Jòhánnù 3:18.

  45. Wo Orin Dáfídì 40:11.

  46. Wo Romù 8:16.

  47. Wo 1 Sámúẹ́lì 2:3; Matteu 6:8; 2 Néfì 2:24; 9:20.

  48. Wo Gẹ́nẹ́sísì 17:1; Jeremíàh 32:17; 1 Néfì 7:12; Álmà 26:35.

  49. Wo Jeremíàh 31:3; 1 Jòhánnù 4:7–10; Álmà 26:37.

  50. Wo 2 Néfì 9; Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 20:17–31; Mósè 6:52–62.

  51. Wo Jòhánnù 3:16; 1 Jòhánnù 4:9–10.

  52. Wo Jòhánnù 8:29; 3 Néfì 27:13.

  53. Wo Jòhánnù 15:12; 1 Jòhánnù 3:11.

  54. Wo Lúkù 22:39–46.

  55. Wo Jòhánnù 19:16–30.

  56. Wo Jòhánnù 20:1–18.

  57. Wo 1 Kọ́ríntì 15:20–22; Mòsíà 15:20–24; 16:7–9; Ẹkọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 76:16–17.

  58. Wo Ìṣe Àwọn Àpóstélì 11:17–18; 1 Timothy 1:14–16; Álmà 34:8–10; Moroni 6:2–3, 8; Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 19:13–19.

  59. Wo Matteu 11:28–30; 2 Kọ́rintì 12:7–10; Philippians 4:13; Alma 26:11–13.

  60. Wo Matteu 16:18–19; Éfésù 2:20.

  61. Wo Máttéù 24:24; Ìṣe 20:28–30.

  62. Wo Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 20:1–4; 21:1–7; 27:12; 110; 135:3; Joseph Smith—History 1:1–20.

  63. Wo Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 1:14, 38; 43: 1–7; 107:91–92.